Àfiwé owó oṣù àwọn ṣọ́jà Nàìjíríà pẹ̀lú àwọn akẹgbẹ́ wọn lórílẹ̀èdè míràn ní Áfíríkà

Oríṣun àwòrán, HQ Nigerian Army
Agbẹnusọ nigbakan ri fun ileeṣẹ ọmọogun orilẹede Naijiria, Ọgagunfẹyinti John Enenche ti pe fun afikun owo oṣu awọn ọmọogun lorilẹede Naijiria, o ni owo oṣu ọmọogun to kere julọ yẹ ko jẹ ẹgbẹrun lọna igba ati aadọta Naira, N250, 000 ni ibamu pẹlu bi nnkan ṣe ri lọwọ yii lorilẹede Naijiria ati bi wọn ṣe n fori laku .
Minisita fun eto abo, Ọgagunfẹyinti Chris Musa lo kọkọmu ọrọ nipa igbayegbadun awọn ṣọja wa si ojutaye laipẹ yii nigba to kede pe wọn ti ṣe afikun owo oṣu awọn ṣọja to kere julọ si ẹgbẹrun lọna ọgọrun Naira, (N100, 000) lati ẹgbẹrun mọkandinlaadọta (N49, 000) to wa tẹlẹ.
Nibayii ọrọ ti Ọgagunfẹyinti Enenche sọ nipa owooṣu tuntun yii ti n fa ọpọ awisọ lori ayelujara ti wọn si n kọminu lori owo oṣu awọn ologun pẹlu iṣẹ ifaraẹnijin ti wọn n ṣe lẹnu i'sẹ lati daabo bo ilu, paapaa fifi ori la iku lati koju awọn agbebọn ati agbesunmọmi kaakiri tibutoro Naijiria.
Afiwe laarin Owo oṣu awọn ṣọja lorilẹede Naijiria ati awọn akẹgbẹ wọn lawọn orilẹede yoku nilẹ Afirika

Oríṣun àwòrán, HQ Nigerian Army
Ko si akọsilẹ apapọ kan gboogi fun afiwe owo oṣu awọn ologun ati igbayegbadun wọn ni Afirika. Ni awọn orilẹede kan, ko tilẹ si iroyin to kuna nipa rẹ ni ita gbangba fun araalu lati mọ.
Amọ, awọn ajọ kan wa ti ojuṣe wọn duro lori akojọ awọn iroyin wọnyi niwọba eyi ti wọn ba le ri kojọ.
Eyi ni iye owo to kere ju gẹgẹbi owooṣu ologun ni Naijiria, South Africa ati Ghana gẹgẹbi ajọ ako iṣiro iwadi jọ Statisense lorilẹede Naijiria ṣe fi sita.
Fun ṣọja ti ipo rẹ jẹ 'Private' –
Naijiria: ₦104,000 ($64)
Ghana: GHS 1,000 to 1,500 (₦157,000 – ₦235,000)
South Africa: R8,000 to R12,000 (₦704,000 – ₦1.06 Million)

Oríṣun àwòrán, HQ Nigerian Army
Bakan naa ni Statisense tun ṣalaye lori owo oṣu awọn ọgagun onirawọ meji (Major General) eyi ti wọn fi si Miliọnu kan o le ẹẹdẹgbẹjọ Naira, (N1.15m).
Owo oṣu akẹgbẹ wọn lorieede South Africa ju eyi lọ ni ilọpo mẹjọ pẹlu R120,000 tabi ₦9,999,600 iyẹn owoto din diẹ ni miliọnu mẹwaa Naira ni ibamu pẹlu odiwọn owo Naira lode oni.
BBC News Yoruba ko tii fi idi awọn owo wọnyi mulẹ ni iha ọdọ tiwa o, amọṣa. orilẹede Naijiria ati South Africa wa lara awọn orilẹede marun un ti ọrọ aje wọn ṣe jọmujọmu julọ ni Afirika.





























