Fàákája láàrin ọlọ́pàá àti iléeṣẹ́ ọmogun oju-omi l'Osun lórí àwọn jàndùkú tó fẹ́ gba gáréèjì, àwọn tọ́ọ̀gì tún jí káàdì ìdìbò kó lọ

Ọga ọlọpaa Tunji Disu wọ aṣọ 
ọlọpaa pẹlu fila, Gomina Ademola Adeleke wọ aṣọ olomi buluu pẹlu awo loju rẹ

Oríṣun àwòrán, Gov Ademola Adeleke

Published
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 4

Rogbodiyan to n ṣẹlẹ nipinlẹ Osun ṣaaju eto idibo gomina to n bọ si n tẹsiwaju lẹyin ti a gbọ pe awọn jabduku yawọ wọọdu INEC to wa nile ẹkọ Oyinlola DC School ni Okuku nibi ti wọn ji kaadi idibo ti ajọ naa n pin atawọn nnkan mii lọ.

Iṣẹlẹ yii ni a gbọ pe o ṣakoba fawọn osiṣẹ INEC ti wọn pin kaadi idibo tori onikaluku fẹsẹ fẹ lẹyin tawọn janduku ọhun de.

Olugbe ilu Okuku kan, Gbadebo, sọ fawọn akọroyin pe ṣadeede lawọn janduku naa ya wọ ile ẹkọ ti INEC ti n pin kaadi idibo naa.

Gbadebọ ni awọn janduku ọhun yinbọ soke bi wọn ti ji awọn kaadi idibo to wa lori aga ko lọ.

Olugbe ilu Okuku naa sọ pe awọn janduku ọhun to mẹjọ ti ya wọ ile ẹkọ ti ajọ INEC ti n pin kaadi idibo.

Ẹwẹ, agbenusọ fun ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Osun, Abiodun Ojelabi, sọ pe Kọmiṣọna ọlọpaa Ibrahim Gotan ti bẹnu ẹtẹ lu iṣẹlẹ naa.

Ojelabi fikun ọrọ rẹ pe kọmisọna ọlọpaa ti paṣẹ iwadii kikun lori iṣẹlẹ ọhun, ati pe o fẹ kawọn to wa nidii naa oju wina ofin.

Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa tun fi dawọn araalu loju wi pe awọn ọlọpaa ko ni kaarẹ lati maa tẹle ofin bi wọn ṣe n ṣiṣẹ wọn.

Bakan naa ni o rọ awọn araalu lati ma fọwọ pada ofin loju.

Ọlọpaa ṣekọlu sawọn ọmogun oju omi lati tu Asiri Eniba atawọn mii silẹ - Ijọba Osun

Skip podcast promotion and continue reading
Èyí ni ìkànnì Whatsapp wa

Àjáàbalẹ̀ ìròyìn BBC News Yorùbá lórí WhatsApp rẹ

Darapọ̀ mọ́ wa nibì

End of podcast promotion

Ẹwẹ, ijọba ipinlẹ Osun ti fẹsun kan ileeṣẹ ọlọpaa wi pe wọn ṣe ikọlu si ọmogun oju-omi kan niluu Ile-Ife lana ọjọ Aiku ọjọ kẹrindinloọgbọn oṣu Keje yii lati tu Kazeem Oyewale tawọn eeyan mọ si Asiri Eniba silẹ.

Ijọba ipinlẹ Osun ṣapejuwe iṣẹlẹ naa gẹgẹ bi eyi to lewu fun eto aabo ipinlẹ naa, nigba ti o kepe Aarẹ Bola Tinubu ati oludamọran aarẹ lori eto aabo, Nuhu Ribadu lati dasi ọrọ naa.

Iṣẹlẹ yii waye lẹyin wakati diẹ tawọn janduku kan fẹ fipa gba ibudokọ kan lagbegbe Mayfair niluu Ile-Ife nibi tawọn ti fẹsẹ fẹ nigba ti ibọn n dun lakọ lakọ.

Ohun ti a gbọ ni pe awọn ologun ko gba fawọn janduku naa lati ri ibudokọ naa gba.

Ninu ọrọ rẹ, kọmiṣọna fun eto iroyin ati ilanilọyẹ nipinle Osun, Kolapo Alimi, so pe awọn ọlọpaa tẹle Eniba atawọn janduku ti wọn fẹ gba ibudokọ naa.

Ariwo awọn eeyan ilu Ile-Ife ni a gbọ pe ileeṣẹ ọmogun oju omi gbọ ti wọn fi fọwọ ofin mu awọn janduku marun un naa.

Ijọba tun fẹsun kan komiṣọna pe oun lo pe ileeṣẹ ọmogun oju-omi lori foonu lati tu awọn janduku naa silẹ, amọ, ileeṣẹ ọmogun oju omi sọ pe ayafi ti aṣẹ ba wa lati oke lawọn le tu wọn silẹ.

Lẹyin naa nijọba ipinlẹ Osun sọ pe kọmiṣọna ọlọpaa fi ọkọ mẹrin ko awọn ọlọpaa lati lọ ṣekọlu si ọmogun oju-omi kan.

A gbọ pe awọn ọlọpaa naa yin tajutaju sawọn ọmogun oju omi naa lati fipa tu awọn janduku ọhun silẹ.

Bakan naa ni a tun gbọ pe awọn ọlọpaa ko gba ibọn to wa lọwọ awọn janduku naa nigba ti awọn ọmogun oju omi fọwọ ofin mu wọn.

Iṣẹlẹ yii lo tun jẹ tuntun ninu rogbodiyan to n waye nipinlẹ Osun ṣaaju eo idibo gomina ọjọ kẹẹdogun oṣu Kẹjọ to n bọ.